1. Bí Jésù ti ń kúrò ni tẹ́ḿpílì, àwọn ọmọ-ẹ̀yin rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n fẹ́ fi ẹwà tẹ́ḿpílì náà hàn án.
2. Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin kò ha rí gbogbo nǹkan wọ̀nyí? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín gbogbo ilé yìí ni a óò wó lulẹ̀, kò ní sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí òmíràn, tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
3. Bí ó ti jókòó ní orí òkè Ólífì, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tọ̀ ọ́ wá ní kọ̀kọ̀, wọ́n wí pé, “Sọ fún wa nígbà wo ni èyí yóò ṣẹlẹ̀? Kí ni yóò jẹ́ àmì ìpadàwá rẹ, àti ti òpin ayé?”