Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 22:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jésù tún fi òwe sọ̀rọ̀ fún wọn wí pé:

2. “Ìjọba ọ̀run dàbí ọba kan ti ó múra àṣè ìgbéyàwó ńlá fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.

3. Ó rán àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti lọ sọ fún àwọn tí a ti pè tẹ́lẹ̀ pé àsìkò ti tó láti wá sí ibi àsè. Ṣùgbọ́n gbogbo wọn kọ̀ láti wá.

4. “Lẹ́yìn náà ó tún rán àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ mìíràn pé, ‘Ẹ sọ fún àwọn tí mo ti pè wí pé, mo ti se àsè náà tán. A pa màlúù àti ẹran àbọ́pa mi, a ti ṣe ohun gbogbo tán, ẹ wa sí ibi àsè ìgbéyáwó.’

5. “Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó ránṣẹ́ lọ pè kò kán á si. Wọ́n ń bá iṣẹ́ wọn lọ, ọ̀kan sí ọ̀nà oko rẹ̀, òmíràn sí ibi òwò rẹ̀.”

6. Àwọn ìyókù sì lu àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n ta àbùkù fún wọn, wọ́n lù wọ́n pa.

7. Ọba yìí bínú gidigidi, ó sì rán àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, ó sì pa àwọn apànìyàn náà run, ó sì jó ìlú wọn

8. “Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Àsè ìgbéyàwó ti ṣe tàn, ṣùgbọ́n àwọn tí a pè kò yẹ fún ọlá náà.

Ka pipe ipin Mátíù 22