Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 20:28-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Gẹ́gẹ́ bí Ọmọ-Ènìyàn kò ṣe wá sí ayé, kí ẹ lè ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún yín, àti láti fi ẹ̀mí rẹ ṣe ìràpadà ọ̀pọ̀ ènìyàn.”

29. Bí Jésù àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti ń fi ìlú Jẹ́ríkò sílẹ̀, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì wọ́ tẹ̀lé e lẹ́yìn.

30. Àwọn ọkùnrin afọ́jú méjì sì jókòó lẹ́bàá ọ̀nà, nígbà tí wọ́n sí gbọ́ pé Jésù ń kọjá lọ, wọ́n bẹ̀rẹ̀ síí kígbe pé, “Olúwa, Ọmọ Dáfídì, ṣàánú fún wa!”

31. Àwọn ènìyàn sí bá wọn wí pé kí wọn dákẹ́, ṣùgbọ́n wọ́n kígbe sóke sí i. “Olúwa, ọmọ Dáfídì, ṣàánú fún wa!”

32. Jésù dúró lójú ọ̀nà, ó sì pè wọ́n pé, Ó béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin fẹ́ kí èmi ṣe fún yín?”

33. Wọ́n dáhùn pé, “Olúwa, àwa fẹ́ kí a ríran.”

34. Àánú wọn sì ṣe Jésù, ó fi ọwọ́ kan ojú wọn. Lójú kan náà, wọ́n sì ríran, wọ́n sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.

Ka pipe ipin Mátíù 20