Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 2:15-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. ó sì wà níbẹ̀ títítí Hẹ́rọ́dù fi kú. Èyí jẹ́ ìmúṣẹ àṣọtẹ́lẹ̀ ohun tí Olúwa sọ láti ẹnu wòlíì pé: “Mo pe ọmọ mi jáde láti Éjíbítì wá.”

16. Nígbà tí Hẹ́rọ̀dù rí í pé àwọn amòye náà ti tan òun jẹ, ó bínú gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù àti ní ẹkùn rẹ̀ láti àwọn ọmọ ọdún méjì sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àkókò tí ó ti fi ẹ̀sọ̀ ẹ̀sọ̀ béèrè lọ́wọ́ àwọn amòye náà.

17. Nígbà náà ni èyí tí a ti sọ tẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Jeriemáyà wá sẹ pé:

18. “A gbọ́ ohùn kan ní Rámà,Ohùn réré ẹkún àti ọ̀fọ̀ ńláRákélì ń sọkùn àwọn ọmọ rẹ̀Ó kọ̀ láti gbìpẹ̀nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ tí kò sí mọ́.”

19. Lẹ́yìn ikú Hẹ́rọ́dù, ańgẹ́lì Olúwa fara hàn Jósẹ́fù lójú àlá ní Éjíbítì

20. Ó sì wí fún un pé, “Dìde gbé ọmọ-ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ padà sí ilẹ̀ Ísírẹ́lì, nítorí àwọn tí ń wá ọmọ-ọwọ́ náà láti pa ti kú.”

21. Nítorí náà, Ó sì dìde, ó gbé ọmọ-ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ ó sì wá sí ilẹ̀ Ísírẹ́lì.

22. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó gbọ́ pé Ákílọ́sì ni ó ń jọba ní Jùdíà ní ipò Hẹ́rọ́dù baba rẹ̀, ó bẹ̀rù láti lọ sí ì bẹ̀. Nítorí tí Ọlọ́run ti kìlọ̀ fún un ní ojú àlá, ó yí padà, ó sì gba ẹkùn Gálílì lọ,

23. ó sì lọ í gbé ní ìlú tí a pè ní Násárẹ́tì. Nígbà náà ni èyí tí a sọ tẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì wá sí ìmúṣẹ: “A ó pè é ní ará Násárẹ́tì.”

Ka pipe ipin Mátíù 2