Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 19:2-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì mú wọn láradá níbẹ̀.

3. Àwọn Farisí wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti dán an wò. Wọ́n bi í pé, “Ǹjẹ́ ó tọ̀nà fún ọkùnrin láti kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nítorí ohunkóhun?”

4. Ó dáhùn pé, “A ti rí i kà pé ‘ní ìpilẹ̀sẹ, Ọlọ́run dá wọn ni ọkùnrin àti obìnrin.’

5. Ó sì wí fún un pé, Nítorí ìdí èyí ‘Ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sí da ara pọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì náà á sì di ara kan.’

6. Wọn kì í tún ṣe méjì mọ́, ṣùgbọ́n ara kan. Nítorí náà, ohun tí Ọlọ́run bá ti so ṣọ̀kan, kí ẹnikẹ́ni má ṣe yà wọ́n.”

7. Wọ́n bi í pé: “Kí ni ìdí tí Mósè fi pàṣẹ pé, ọkùnrin kan lè kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nípa fífún un ní ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀?”

8. Jésù dáhùn pé, “Mósè yọ̀ǹda kí ẹ kọ aya yín sílẹ̀ nítorí ọkàn yín le. Ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ láti àtètèkọ́ṣe.

9. Mo sọ èyí fún yín pé, ẹni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, láìṣe pé nítorí àgbèrè, tí ó sì fẹ́ òmíràn, ó ṣe panṣágà.”

10. Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Bí ọ̀rọ̀ bá rí báyìí láàrin ọkọ àti aya, kó ṣààfààní fún wa láti gbé ìyàwó.”

Ka pipe ipin Mátíù 19