Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 16:25-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ gba ẹ̀mí rẹ̀ là, yóò sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ẹ̀mí rẹ̀ nítorí mi, yóò rí i.

26. Èrè kí ni ó jẹ́ fún ènìyàn bí ó bá jèrè gbogbo ayé yìí, tí ó sì sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù? Tàbí kí ni ènìyàn yóò fi dípò ẹ̀mí rẹ̀?

27. Nítorí Ọmọ ènìyàn yóò wá nínú ogo baba rẹ pẹ̀lú àwọn ańgẹ́lì rẹ̀, nígbà náà ni yóò sì san án fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.

28. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín. Ẹlòmíràn wà nínú àwọn tí ó níhìn-ín yìí, tí kì yóò ri ikú títí wọn ó fi rí ọmọ-ènìyàn tí yóò máa bà ní ìjọba rẹ̀.”

Ka pipe ipin Mátíù 16