Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 10:36-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Ará ilé ènìyàn ni yóò sì máa ṣe ọ̀tá rẹ̀.’

37. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ràn bàbá rẹ̀ tàbí ìyá rẹ̀ jù mí lọ kò yẹ ní tèmi, ẹnikẹ́ni tí ó ba fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin jù mí lọ kò yẹ ní tèmi;

38. Ẹnikẹ́ni tí kò bá gbé àgbélébùú rẹ̀ kí ó tẹ̀ lé mi kò yẹ ní tèmi.

39. Ẹni tí ó bá rí ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ ẹ̀mí rẹ̀ nú nítorí tèmi ni yóò rí i.

40. “Ẹni tí ó bá gbà yín, ó gbà mí, ẹni tí ó bá sì gbà mí gba ẹni tí ó rán mi.

Ka pipe ipin Mátíù 10