Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 10:33-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sẹ́ mí ní níwájú àwọn ènìyàn, òun náà ni èmi náà yóò sọ wí pé n kò mọ̀ níwájú Baba mi ní ọ̀run.

34. “Ẹ má ṣe rò pé mo mú àlàáfíà wá sí ayé, Èmi kò mú àlàáfíà wá bí kò ṣe idà.

35. Nítorí èmi wá láti“ ‘ọmọkùnrin ní ipa sí bàbá rẹ̀,ọmọbìnrin ní ipa sí ìyá rẹ̀,àti aya ọmọ sí ìyakọ rẹ̀…

36. Ará ilé ènìyàn ni yóò sì máa ṣe ọ̀tá rẹ̀.’

37. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ràn bàbá rẹ̀ tàbí ìyá rẹ̀ jù mí lọ kò yẹ ní tèmi, ẹnikẹ́ni tí ó ba fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin jù mí lọ kò yẹ ní tèmi;

38. Ẹnikẹ́ni tí kò bá gbé àgbélébùú rẹ̀ kí ó tẹ̀ lé mi kò yẹ ní tèmi.

39. Ẹni tí ó bá rí ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ ẹ̀mí rẹ̀ nú nítorí tèmi ni yóò rí i.

40. “Ẹni tí ó bá gbà yín, ó gbà mí, ẹni tí ó bá sì gbà mí gba ẹni tí ó rán mi.

41. Ẹni tí ó ba gba wòlíì, nítorí pé ó jẹ́ wòlíì yóò jẹ èrè wòlíì, ẹni tí ó bá sì gba olódodo nítorí ti ó jẹ́ ènìyàn olódodo, yóò jẹ èrè olódodo.

42. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ago omi tútú fún ọ̀kan nínú àwọn onírẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí mu nítorí tí ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi, ọ̀títọ́ ni mo wí fún yín, kò ní pàdánù èrè rẹ̀.”

Ka pipe ipin Mátíù 10