Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 3:5-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká pẹ̀lú ìbínú, ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí líle àyà wọn, ó sọ fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ jáde.” Ó nà án jáde, ọwọ́ náà sì bọ̀ sípò padà pátápátá.

6. Lójúkan-náà, àwọn Farisí jáde lọ, láti bá àwọn ọmọ ẹ̀yin Hẹ́rọ́dù gbìmọ̀ pọ̀, bí wọn yóò ṣe pa Jésù.

7. Jésù pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ yẹra kúrò níbẹ̀ lọ sí etí òkun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Gálílì àti Jùdíà sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.

8. Nígbà tí wọ́n gbọ́ ìrpyìn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá láti Jùdíà, Jerúsálémù àti Ìdúmíà, àti láti apákejì odò Jọ́dání àti láti ihà Tírè àti Ṣídónì.

9. Nítorí ẹ̀rọ̀, Jésù sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Rẹ̀ lati sètò ọkọ̀ ojú omi kekere kan sílẹ̀ fún un láti lọ, láti lé àwọn ẹ̀rọ̀ sẹ́yìn.

10. Nítorí tí ó mú ọ̀pọ̀ ènìyàn láradá lọ́jọ́ náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn aláìsàn ló yí i ká, tí wọ́n sì ń gbìyànjú láti fi ọwọ́ kàn án.

11. Ìgbàkúùgbà tí àwọn tí ó kún fún ẹ̀mí àìmọ́ bá ti fojú gán-án ní rẹ̀, wọ́n á wólẹ̀ níwájú rẹ̀. Wọn a sì kígbe lóhùn-rara wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run.”

12. Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn gidigidi, kí wọn má ṣe fi òun hàn.

13. Jésù gun orí òkè lọ ó gun orí òkè lọ, ó sì pe àwọn kan tí ó yàn láti wà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.

14. Ó yan àwọn méjìlá-ó pè wọ́n ní apostẹli-kí wọ́n kí ó lè wà pẹ̀lú rẹ̀, àti kí wọn kí ó lè lọ láti wàásù

15. àti láti lágbára láti lé àwọn ẹ̀mí Èsù jáde.

16. Wọ̀nyí ni àwọn méjìlá náà tí ó yàn, Ṣímóní (ẹni ti ó sọ àpèlé rẹ̀ ní Pétérù)

17. Jákọ́bù ọmọ Sébédè àti Jòhánù arákùnrin rẹ̀ (àwọn ẹni tí Jésù sọ àpèlé wọ́n ní Bóánájì, èyí tí ó túmọ̀ sí àwọn ọmọ àrá).

18. Àti Ańdérù, Fílípì, Bátólómíù, Mátíù, Tómásì, Jákọ́bù (ọmọ Álíféù), Tádéù, Símónì (ọ̀kan nínú àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú tí ó fẹ́ ará Kénánì tí ó fi ìjàngbọ̀n dojú ìjọba Rómù bolẹ̀)

19. Àti Júdásì Ísíkáríọ́tù, ẹni tí ó fi í hàn níkẹyìn.

20. Nígbà náà ni Jésù sì wọ inú ilé kan, àwọn ẹ̀rọ̀sì tún kórájọ, tó bẹ́ẹ̀ tí Òun àti àwọn Ọmọ-ẹ̀yin rẹ̀ kò rí ààyè láti jẹun.

21. Nígbà tí àwọn ẹbí rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wá láti mu un lọ ilé, nítorí tí wọn wí pé, “Orí rẹ̀ ti dàrú.”

22. Àwọn olùkọ́ni-ni-òfin ṣọkàlẹ̀ wá láti Jérúsálẹ́mù, wọn sì wí pé, “Ó ni Béélísébúbù, olórí àwọn ẹ̀mí Èṣù, ni ó sì fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde!”

23. Jésù pè wọ́n, ó sì fi òwé bá wọn sọ̀rọ̀: “Báwo ni Èsù ṣe lè lé èsù jáde?

Ka pipe ipin Máàkù 3