Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 14:66-72 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

66. Ní àkókò yìí Pétérù wà ní ìṣàlẹ́ inú àgbàlá ilé ìgbẹ́jọ́. Nínú àgbàlá yìí, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́-bìnrin àlùfáà àgbà kíyèsí í tí Pétérù ń yáná.

67. Nigba tí ó rí Pétérù tí ó ti yáná, Ó tẹjú mọ́ ọn, ó sì sọ gbangba pé,“Ìwọ pàápàá wà pẹ̀lú Jésù ara Násárẹ̀tì.”

68. Ṣùgbọ́n Pétérú ṣẹ́, ó ni, “N kò mọ Jésù náà rí; ohun tí ó ń sọ yìí kò tilẹ̀ yé mi.” Pétérù sì jáde lọ sí ẹnu ọ̀nà àgbàlá ilé ìgbẹ́jọ́. Àkùkọ sì kọ.

69. Ọmọbìnrin yẹn sì tún rí Pétérù. Ó sì tún bẹ̀rẹ̀ sí wí fún àwọn tí wọ́n dúró níbẹ̀. Ó ní, “Ọkùnrin yìí gan an jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jésù.”

70. Ṣùgbọ́n Pétérù tún ṣẹ́.Nígbà tí ó sí tún ṣẹ díẹ̀ sí i, àwọn tí wọ́n dúró lẹ́gbẹ́ Pétérù wá wí fún un pé, “Láìṣe àní àní, ara wọn ni ìwọ. Nítorí ará Gálílì ni ìwọ náà.”

71. Nígbà náà ni Pétérù bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ́ ó sì ń búra, ó ni, “N kò mọ ẹni ti ẹ ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ yí rí!”

72. Lójú kan náà tí àkùkọ yìí kọ lẹ́ẹ̀kejì Pétérù rántí ọ̀rọ̀ Jésù fún un pé, “Kí àkùkọ tó kọ lẹ́ẹ̀mejì, ìwọ yóò ṣẹ́ mí nígbà mẹ́ta.” Ó sì rẹ̀ ẹ́ láti inú ọkàn wá, ó sì sọkùn.

Ka pipe ipin Máàkù 14