1. Bí wọ́n ti súnmọ́ Bẹ́tífágè àti Bẹ́tanì ní ẹ̀yìn odi ìlú Jerúsálémù, wọ́n dé orí òkè ólífì. Jésù rán méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ṣíwájú.
2. Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí abúlé tó wà lọ́hùn-ún nì. Nígbà tí ẹ bá sì wọlé, ẹ̀yin yóò rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a so mọ́lẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò ì tí i gùn rí. Ẹ tú u, kí ẹ sì mú wá síhìn-ín.