Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 8:50-56 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

50. Ṣùgbọ́n nígbà tí Jésù gbọ́, ó dá a lóhùn, pé, “Má bẹ̀rù: sá gbàgbọ́ nìkan, a ó sì mú un láradá.”

51. Ṣùgbọ́n nígbà tí Jésù sì wọ ilé, kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni wọlé, bí kò ṣe Pétérù, àti Jákọ́bù, àti Jòhánù, àti baba àti ìyá ọmọbìnrin náà.

52. Gbogbo wọn sì sọkún, wọ́n pohùnréré ẹkún rẹ̀: ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má sọkún mọ́; kò kú, sísùn ni ó sùn.”

53. Wọ́n sì fi í ṣẹ̀fẹ̀, wọ́n sá mọ̀ pé ó kú.

54. Nígbà tí ó sì sé gbogbo wọn mọ́ òde, ó mú un lọ́wọ́, ó sì wí pé, “Ọmọbìnrin, dìde!”

55. Ẹ̀mí rẹ̀ sì padà bọ̀, ó sì dìde lọ́gán: ó ní kí wọn fún un ní oúnjẹ.

56. Ẹnu sì ya àwọn òbí rẹ̀: ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn pé, kí wọn má ṣe wí fún ẹnìkan ohun tí a ṣe.

Ka pipe ipin Lúùkù 8