Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 3:15-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń retí, tí gbogbo wọn sì ń rò nínú ara wọn nítorí Jòhánù, bí òun ni Kírísítì bí òun kọ́;

16. Jòhánù dáhùn ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Lóòótọ́ ni èmi ń fi omi bamtíìsì yín; ṣùgbọ́n ẹni tí ó lágbára jù mí lọ ńbọ̀, okùn bàtà ẹ̀ṣẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ítú: òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamtísì yín:

17. Ẹni tí àtẹ rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, láti gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ mọ́ tótó, kí ó sì kó àlìkámà rẹ̀ sínú àká; ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”

18. Jòhánù lo oríìṣíríṣìí ọ̀rọ̀ púpọ̀ láti gba àwọn ènìyàn níyànjú àti láti wàásù ìhìnrere fún wọn.

19. Ṣùgbọ́n nígbà ti Jòhánù bú Hẹ́rọ́dù tetírakì, tí ó bá wí nítorí Hérọ́díà aya Fílípì arákùnrin rẹ̀, àti nítorí ohun búburú gbogbo tí Hẹ́ródù tí ṣe,

20. Ó fi èyí parí gbogbo rẹ̀ ní tí ó fi Jòhánù sínú túbú.

21. Nígbà tí a sì ìtẹ̀bọmi àwọn ènìyàn gbogbo tán, ó sì ṣe, a bamtíìsì Jésù pẹ̀lú, bí ó ti ń gbàdúrà, ọ̀run ṣí sílẹ̀,

22. Ẹ̀mí Mímọ́ sì sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ ní àwọ̀ àdàbà, ohùn kan sì ti ọ̀run wá, tí ó wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ ọmọ mi; ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”

23. Jésù tìkara rẹ̀ ń tó bí ẹni ọgbọ̀n ọdún, nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ (bí a ti fi pè) ọmọ Jósẹ́fù,tí í ṣe ọmọ Élì,

24. Tí í ṣe ọmọ Mátatì,tí í ṣe ọmọ Léfì, tí í ṣe ọmọ Melíkì,tí í ṣe ọmọ Janà, tí í ṣe ọmọ Jóṣẹ́fù,

25. Tí í ṣe ọmọ Matataì, tí í ṣe ọmọ Ámósì,tí í ṣe ọmọ Náúmù, tí í ṣe ọmọ Ésílì,tí í ṣe ọmọ Nágáì,

26. Tí í ṣe ọmọ Máátì,tí í ṣe ọmọ Matatíà, tí í ṣe ọmọ Síméì,tí í ṣe ọmọ Jósẹ́fù, tí í ṣe ọmọ Jódà,

27. Tí í ṣe ọmọ Jóánà, tí í ṣe ọmọ Résà,tí í ṣe ọmọ Sérúbábélì, tí í ṣe ọmọ Sítíélì,tí í ṣe ọmọ Nérì,

28. Tí í ṣe ọmọ Melíkì,tí í ṣe ọmọ Ádì, tí í ṣe ọmọ Kòsámù,tí í ṣe ọmọ Élímadámù, tí í ṣe ọmọ Érì,

Ka pipe ipin Lúùkù 3