Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 24:43-52 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

43. Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.

44. Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé: A ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mósè, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Sáàmù, nípasẹ̀ mi.”

45. Nígbà náà ni ó ṣí wọn níyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.

46. Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: Kí Kírísítì jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ijọ́ kẹ́ta kúrò nínú òkú:

47. Àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀ èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerúsálémù lọ.

48. Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí.

49. Sì kíyèsí i, mo rán ìlérí Baba mi sí yín: ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerúsálémù, títí a ó fifi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”

50. Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Bétanì, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn.

51. Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run.

52. Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerúsálémù pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀:

Ka pipe ipin Lúùkù 24