Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 23:5-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Wọ́n sì túbọ̀ tẹnumọ́ ọn pé, “Ó ń ru ènìyàn sókè, ó ń kọ́ni káàkiri gbogbo Jùdéà, ó bẹ̀rẹ̀ láti Gálílì títí ó fi dé ìhínyìí!”

6. Nígbà tí Pílátù gbọ́ orúkọ Gálílì, ó béèrè bí ọkùnrin náà bá jẹ́ ará Gálílì.

7. Nígbà tí ó sì mọ̀ pé ará ilẹ̀ Hẹ́rọ́dù ni, ó rán an sí Hẹ́rọ́dù, ẹni tí òun tìkárarẹ̀ wà ní Jerúsálémù ní àkókò náà.

8. Nígbà tí Hẹ́rọ́dù, sì rí Jésù, ó yọ̀ gidigidi; nítorí tí ó ti ń fẹ́ rí i pẹ ó sáà ti ń gbọ́ ìhìn púpọ̀ nítorí rẹ̀; ó sì ń retí láti rí i kí iṣẹ́ àmì díẹ̀ ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe.

9. Ó sì béèrè ọ̀rọ̀ púpọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀; ṣùgbọ́n kò da a lóhùn rárá.

10. Àti àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé dúró, wọ́n sì ń fí ẹ̀sùn kàn án gidigidi.

11. Àti Hẹ́rọ́dù pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun rẹ̀, wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọ́n sì ń fi í ṣẹ̀sín, wọ́n wọ̀ ọ́ ní aṣọ dáradára, ó sì rán an padà tọ Pílátù lọ.

12. Pílátù àti Hẹ́rọdù di ọ̀rẹ́ ara wọn ní ijọ́ náà: nítorí látijọ́ ọ̀tá ara wọn ni wọ́n ti jẹ́ rí.

13. Pílátù sì pe àwọn olórí àlúfáà àti àwọn olórí àti àwọn ènìyàn jọ.

14. Ó sọ fún wọn pé, “Ẹyin mú ọkùnrin yìí tọ̀ mí wá, bí ẹni tí ó ń yí àwọn ènìyàn ní ọkàn padà: sì kíyèsí i, èmí wádìí ẹjọ́ rẹ̀ níwájú yín èmi kò sì rí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́wọ́ ọkùnrin yìí, ní gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ẹ̀yin fi ẹ̀sùn rẹ̀ sùn.

15. Àti Hẹ́rọ́dù pẹ̀lú; ó sá rán an padà tọ̀ wá wá; sì kíyèsí i, ohun kan tí ó yẹ sí ikú ni a kò ṣe láti ọwọ́ rẹ̀.

16. Ǹjẹ́ èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀ lọ.”

Ka pipe ipin Lúùkù 23