Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 23:45-54 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

45. Òòrùn sì ṣóòkùn, aṣọ ìkéle ti tẹ́ḿpílì sì ya ní àárin méjì,

46. Nígbà tí Jésù sì kígbe lóhùn rara, ó ní, “Baba, ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé!” Nígbà tí ó sì wí èyí tan, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀.

47. Nígbà tí balógun ọ̀rún rí ohun tí ó ṣe, ó yin Ọlọ́run lógo, wí pé, “Dájúdájú olódodo ni ọkùnrin yìí!”

48. Gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ láti rí ìran yìí, nígbà tí wọ́n rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀ wọ́n lu ara wọn ní oókan àyà, wọ́n sì padà sí ilé.

49. Àti gbogbo àwọn ojúlùmọ̀ rẹ̀, àti àwọn obìnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Gálílì wá, wọ́n dúró lókèrè, wọ́n ń wo nǹkan wọ̀nyí.

50. Sì kíyèsí i, ọkùnrin kan tí a ń pè ní Jóṣẹ́fù, láti ìlú àwọn Júù kan tí ń jẹ́ Arimatíyà. Ó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ìgbìmọ̀, ènìyàn rere, àti olóòótọ́.

51. Òun kò bá wọn fi ohùn sí ìmọ̀ àti ìṣe wọn; òun pẹ̀lú ń retí ìjọba Ọlọ́run.

52. Ọkùnrin yìí tọ Pílátù lọ, ó sì tọrọ òkú Jésù.

53. Nígbà tí ó sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀, ó sì fi aṣọ àlà dì í, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibojì tí a gbẹ́ nínú Òkúta, níbi tí a kò tẹ́ ẹnikẹ́ni sí rí.

54. Ó sì jẹ́ ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́: ọjọ́ ìsinmi sì kù sí dẹ̀dẹ̀.

Ka pipe ipin Lúùkù 23