Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 22:66-71 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

66. Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ìjọ àwọn alàgbà àwọn ènìyàn péjọ pọ̀, àti àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, wọ́n sì fà á lọ sí àjọ wọn, wọ́n ń wí pé,

67. “Bí ìwọ́ bá jẹ́ Kírísítì náà? Sọ fún wa!”Ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo bá wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́;

68. Bí mo bá sì bi yín léèrè pẹ̀lú, ẹ̀yin kì yóò dá mi lóhùn, (bẹ́ẹ̀ ni ẹ kì yóò fi mí sílẹ̀ lọ).

69. Ṣùgbọ́n láti ìsinsinyìí lọ ni ọmọ-ènìyàn yóò jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún agbára Ọlọ́run.”

70. Gbogbo wọn sì wí pé, “Ìwọ ha ṣe Ọmọ Ọlọ́run bí?”Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin wí pé, èmi ni.”

71. Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀rí wo ni àwa tún ń fẹ́ Àwa tìkarawa sáà ti gbọ́ lẹ́nu rẹ̀!”

Ka pipe ipin Lúùkù 22