Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 21:19-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Nínú sùúrù yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.

20. “Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerúsálémù ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.

21. Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Jùdéà sá lọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrin rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbéríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.

22. Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.

23. Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fí ọmú fún ọmọ mu ní ijọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.

24. Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dì wọ́n ní ìgbékùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerúsálémù yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.

25. “Àmì yóò sì wà ní ọ̀run, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpáyà híhó òkun àti ìgbì-omi.

26. Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.

27. Nígbà náà ni wọn ó sì rí ọmọ-ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú ìkùukù àwọ̀sánmà pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.

28. Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”

29. Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsí igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi;

30. Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnrarayín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́rẹ́fẹ́.

31. Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o sẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.

Ka pipe ipin Lúùkù 21