Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 20:31-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Ẹ̀kẹta sì ṣú u lópó: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn méjèèje pẹ̀lú: wọn kò sì fi ọmọ sílẹ̀, wọ́n sì kú.

32. Nígbẹ̀yìn pátápátá obìnrin náà kú pẹ̀lú.

33. Ǹjẹ́ ní àjíǹde òkú, aya tìtani yóò ha ṣe nínú wọn? Nítorí àwọn méjèèje ni ó sáà ni ín ní aya.”

34. Jésù sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Àwọn ọmọ ayé yìí a máa gbéyàwó, wọn a sì máa fa ìyàwó fún-ni.

35. Ṣùgbọ́n àwọn tí a kà yẹ láti jogún ìyè ayérayé náà, àti àjíǹde kúrò nínú òkú, wọn kì í gbéyàwó, wọn kì í sì í fa ìyàwó fún-ni.

36. Nítorí wọn kò lè kú mọ́; nítorí tí wọn bá àwọn áńgẹ́lì dọ́gba; àwọn ọmọ Ọlọ́run sì ni wọ́n, nítorí wọ́n di àwọn ọmọ àjíǹde.

37. Ní ti pé a ń jí àwọn òkú dìde, Mósè tìkararẹ̀ sì ti fihàn ní ìgbẹ́, nígbà tí ó pe Olúwa ni Ọlọ́run Ábúráhámù, àti Ọlọ́run Ísáákì, àti Ọlọ́run Jákọ́bù.

38. Bẹ́ẹ̀ ni òun kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú, bí kò ṣe ti àwọn alààyè: nítorí gbogbo wọn wà láàyè fún un.”

39. Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé dá a lóhùn, pé, “Olùkọ́ ìwọ wí rere!”

40. Wọn kò sì jẹ́ bi í léèrè ọ̀rọ̀ kan mọ́.

41. Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí wọ́n fi ń wí pé, Ọmọ Dáfídì ni Kírísítì?

42. Dáfídì tìkárarẹ̀ sì wí nínú ìwé Psalmu pé:“ ‘JÈHÓFÀ wí fún Olúwa mi pé:“Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi

43. Títí èmi ó fi sọ àwọn ọ̀tá rẹdi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.” ’

Ka pipe ipin Lúùkù 20