29. “Olúwa alágbára, nígbàyí ni o tó jọ̀wọ́ ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ,Ní àlààáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ rẹ:
30. Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
31. Tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
32. Ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà,Àti ògo Ísírẹ́lì ènìyàn rẹ̀.”
33. Ẹnu sì ya Jóṣéfù àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
34. Síméónì sì súre fún wọn, ó sì wí fún Màríà ìyá rẹ̀ pé: “Kíyèsí i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Ísírẹ́lì; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀ òdì sí;