Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kólósè 4:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹyin olúwa, ẹ má a fi èyí tí ó tọ́ tí ó sì dọ́gba fún àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ yín; kí ẹ sì mọ̀ pé ẹ̀yin pẹ̀lú ni owa kan ní ọ̀run.

2. Ẹ fi ara yín jì fún àdúrà gbígbà, kí ẹ ṣọ́ra kí ẹ sì máa dúpẹ́;

3. Ẹ máa gbàdúrà fún wa pẹ̀lú, kí Ọlọ́run lè ṣílẹ̀kùn fún wa fún ọ̀rọ̀ náà, láti máa sọ ohun ìjìnlẹ̀ Kírísítì, nítorí èyí tí mo ṣe wà nínú ìdè pẹ̀lú:

4. Ẹ gbàdúrà pé kí èmí leè máa kéde rẹ̀ kedere gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mi.

5. Ẹ jẹ́ ọlọgbọ́n ni tí bí ẹ ti ń ṣe pẹ̀lú àwọn tí ńbẹ̀ lóde, kí ẹ sì máa ra ìgbà padà.

6. Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yín kí ó dàpọ̀ mọ́ oore-ọ̀fẹ́ nígbà gbogbo, èyí tí a fi iyọ̀ dùn, kí ẹ̀yin kí ó le mọ́ bí ẹ̀yin ó tí máa dá òlúkulùlku ènìyàn lóhùn.

Ka pipe ipin Kólósè 4