Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 9:7-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ó sì wí fún un pé, “Lọ wẹ̀ nínú adágún Sílóámù!” (Ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ yìí ni “rán”). Nítorí náà ó gba ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó wẹ̀, ó sì dé, ó ń ríran.

8. Ǹjẹ́ àwọn aládúgbò àti àwọn tí ó rí i nígbà àtijọ́ pé alágbe ni ó jẹ́, wí pé, “Ẹni tí ó ti ń jókòó ṣagbe kọ́ yìí?”

9. Àwọn kan wí pé òun ni.Àwọn elòmíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ó jọ ọ́ ni.”Ṣùgbọ́n òun wí pé, “Èmi ni.”

10. Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Bá wo ni ojú rẹ ṣe là?”

11. Ó dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Jésù ni ó ṣe amọ̀, ó sì fi kùn mí lójú, ó sì wí fún mi pé, ‘Lọ sí adágún Sílóámù, kí o sì wẹ̀,’ èmi sì lọ, mo wẹ̀, mo sì ríran.”

12. Wọ́n sì wí fún un pé, “Òun náà ha dà?”Ó sì wí pé, “Èmi kò mọ̀.”

13. Wọ́n mú ẹni tí ojú rẹ̀ ti fọ́ rí wá sọ́dọ̀ àwọn Farisí.

14. Ọjọ́ ìsinmi ni ọjọ́ náà nígbà tí Jésù ṣe amọ̀, tí ó sì là á lójú.

15. Nítorí náà àwọn Farisí pẹ̀lú tún bi í léèrè, bí ó ti ṣe ríran. Ọkùnrin náà fèsìì, “Ó fi amọ̀ lé ojú mi, mo sì wẹ̀, báyìí mo sì ríran.”

16. Nítorí náà àwọn kan nínú àwọn Farisí wí pé, “Ọkùnrin yìí kò ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, nítorí tí kò pa ọjọ́ ìsinmi mọ́.”Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Ọkùnrin tí í ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò ha ti ṣe lè ṣe irú iṣẹ́ àmì wọ̀nyí?” Ìyapa sì wà láàárin wọn.

17. Nítorí náà, wọ́n sì tún wí fún afọ́jú náà pé, “Kí ni ìwọ wí nítorí rẹ̀, nítorí tí ó là ọ́ lójú?”Ó sì wí pé, “Wòlíì ní í ṣe.”

18. Nítorí náà àwọn Júù kò gbàgbọ́ nípa rẹ̀ pé ojú rẹ̀ ti fọ́ rí, àti pé ó sì tún ríran, títí wọ́n fi pe àwọn òbí ẹni tí a ti là lójú.

19. Wọ́n sì bi wọ́n léèrè wí pé, “Ǹjẹ́ èyí ni ọmọ yín, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, a bí ní afọ́jú? Báwo ni ó ṣe ríran nísinsin yìí?”

20. Àwọn òbí rẹ̀ dá wọn lóhùn wí pé, “Àwa mọ̀ pé ọmọ wa ni èyí, àti pé a bí i ní afọ́jú:

21. Ṣùgbọ́n bí ó tí ṣe ń ríran nísinsin yìí àwa kò mọ̀; ẹni tí ó là á lójú, àwa kò mọ̀: ẹni tí ó ti dàgbà ni Òun; ẹ bi í léèrè: yóò wí fúnra rẹ̀.”

22. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn òbí rẹ̀ sọ, nítorí tí wọ́n bẹ̀rù àwọn Júù: nítorí àwọn Júù ti fohùn sọ̀kan pé bí ẹnìkan bá jẹ́wọ́ pé Kírísítì ni, wọn ó yọ ọ́ kúrò nínú Sínágọ́gù.

23. Nítorí èyí ni àwọn òbí rẹ̀ fi wí pé, “Ẹni tí ó dàgbà ni Òun, ẹ bi í léèrè.”

Ka pipe ipin Jòhánù 9