Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 9:10-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Bá wo ni ojú rẹ ṣe là?”

11. Ó dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Jésù ni ó ṣe amọ̀, ó sì fi kùn mí lójú, ó sì wí fún mi pé, ‘Lọ sí adágún Sílóámù, kí o sì wẹ̀,’ èmi sì lọ, mo wẹ̀, mo sì ríran.”

12. Wọ́n sì wí fún un pé, “Òun náà ha dà?”Ó sì wí pé, “Èmi kò mọ̀.”

13. Wọ́n mú ẹni tí ojú rẹ̀ ti fọ́ rí wá sọ́dọ̀ àwọn Farisí.

14. Ọjọ́ ìsinmi ni ọjọ́ náà nígbà tí Jésù ṣe amọ̀, tí ó sì là á lójú.

15. Nítorí náà àwọn Farisí pẹ̀lú tún bi í léèrè, bí ó ti ṣe ríran. Ọkùnrin náà fèsìì, “Ó fi amọ̀ lé ojú mi, mo sì wẹ̀, báyìí mo sì ríran.”

16. Nítorí náà àwọn kan nínú àwọn Farisí wí pé, “Ọkùnrin yìí kò ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, nítorí tí kò pa ọjọ́ ìsinmi mọ́.”Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Ọkùnrin tí í ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò ha ti ṣe lè ṣe irú iṣẹ́ àmì wọ̀nyí?” Ìyapa sì wà láàárin wọn.

17. Nítorí náà, wọ́n sì tún wí fún afọ́jú náà pé, “Kí ni ìwọ wí nítorí rẹ̀, nítorí tí ó là ọ́ lójú?”Ó sì wí pé, “Wòlíì ní í ṣe.”

18. Nítorí náà àwọn Júù kò gbàgbọ́ nípa rẹ̀ pé ojú rẹ̀ ti fọ́ rí, àti pé ó sì tún ríran, títí wọ́n fi pe àwọn òbí ẹni tí a ti là lójú.

Ka pipe ipin Jòhánù 9