Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 8:54-59 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

54. Jésù dáhùn wí pé, “Bí mo bá yin ara mi lógo, ògo mi kò jẹ́ ǹkan; Baba mi ni ẹni tí ń yìn mí lógo, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, Ọlọ́run yín ní i ṣe:

55. Ẹ kò sì mọ̀ ọ́n: ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n: bí mo bá sì wí pé, èmi kò mọ̀ ọ́n, èmi yóò di èké gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin: ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, mo sì pa ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́.

56. Ábúráhámù baba yín yọ̀ láti rí ọjọ́ mi: ó sì rí i, ó sì yọ̀.”

57. Nítorí náà, àwọn Júù wí fún un pé, “Ọdún rẹ kò ì tó àádọ́ta, ìwọ sì ti rí Ábúráhámù?”

58. Jésù sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kí Ábúráhámù tó wà, èmi nìyìí.”

59. Nítorí náà wọ́n gbé òkúta láti sọ lù ú: ṣùgbọ́n Jésù fi ara rẹ̀ pamọ́, ó sì jáde kúrò ní tẹ́ḿpílì.

Ka pipe ipin Jòhánù 8