Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 4:47-54 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

47. Nígbà tí ó gbọ́ pé Jésù ti Jùdéà wá sí Gálílì, ó tọ̀ ọ́ wá, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, kí ó lè sọ̀kalẹ̀ wá kí ó mú ọmọ òun láradá: nítorí tí ó wà ní ojú ikú.

48. Nígbà náà ni Jésù wí fún u pé, “Bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá rí àmì àti iṣẹ́ ìyanu, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́ láé.”

49. Ọkùnrin ọlọ́lá náà wí fún un pé, “Olúwa, sọ̀kalẹ̀ wá kí ọmọ mi tó kú.”

50. Jésù wí fún un pé, “Má a bá ọ̀nà rẹ lọ; ọmọ rẹ yóò yè.”

51. Bí ó sì ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pàde rẹ̀, wọ́n sì wí fún un pé, ọmọ rẹ ti yè.

52. Nígbà náà ni ó béèrè wákàtí tí ara rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í yá lọ́wọ́ wọn, wọ́n sì wí fún un pé, “Ní àná, ní wákàtí kéje ni ibà náà fi í sílẹ̀.”

53. Bẹ́ẹ̀ ni baba náà mọ̀ pé ọmọ rẹ̀ yè: Òun tìkara rẹ̀ sì gbàgbọ́, àti gbogbo ilé rẹ̀.

54. Èyí ni iṣẹ́ àmì kéjì tí Jésù ṣe nígbà tí ó ti Jùdéà jáde wá sí Gálílì.

Ka pipe ipin Jòhánù 4