Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jákọ́bù 1:21-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Nítorí náà, ẹ lépa láti borí gbogbo èérí àti ìwà búburútí ó gbilẹ̀ yíka, kí ẹ sì fi ọkàn tútù gba ọ̀rọ̀ náà tí a gbìn, tí ó lè gba ọkàn yín là.

22. Ẹ maa kan jẹ́ olùgbọ́ ọ̀rà náà lásán, kí ẹ má baà tipa èyí tan ara yín jẹ́. Ẹ ṣse ohun tí ó sọ.

23. Nítorí bí ẹnikẹ́ni bá jẹ́ olùgbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí kò sì jẹ́ olùṣe, òun dàbí ọkùnrin tí ó ń ṣàkíyèsí ojú ara rẹ̀ nínú díńgí

24. Nítorí, lẹ́yìn tí ó bá ti sàkíyèsí ara rẹ̀, tí ó sì bá tirẹ̀ lọ, lójú kan náà òun sì gbàgbé bí òun ti rí.

25. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń wo inú òfin pípé, òfin òmìnira ni, tí ó sì dúró nínú rẹ̀, tí òun kò sì jẹ́ olùgbọ́ tí ń gbàgbé bí kò ṣe olùṣe rẹ̀, òun yóò jẹ́ alábùkún nínú iṣẹ́ rẹ̀.

26. Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ń sin Ọlọ́run nígbà tí kò kó ahọ́n rẹ̀ ní ìjánu, ó ń tan ọkàn ara rẹ̀ jẹ, ìsìn rẹ̀ sì jẹ́ asán.

27. Ìsìn mímọ́ àti aláìléèérí níwájú Ọlọ́run àti baba ni èyí, láti máa bojú tó àwọn aláìní-baba àti àwọn opó nínú ìpọ́njú wọn, àti láti pa ara rẹ̀ mọ́ láì lábàwọ́n kúrò nínú ayé.

Ka pipe ipin Jákọ́bù 1