Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 21:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ó sì wọn odi rẹ̀ ó jẹ̀ ogóje ìgbọ̀nwọ́ lé mẹ́rin (144), gẹ́gẹ́ bí òṣùwọ̀n ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni tí ańgẹ́lì náà.

18. A sì fi Jásípérì mọ odi ìlú náà. Ìlú náà sì jẹ́ kìkì wúrà, ó dàbí dígí tí o mọ́ kedere.

19. A fi onírúuru òkúta iyebíye ṣe ìpìlẹ̀ ògiri ìlú náà lọ́ṣọ̀ọ́. Ìpìlẹ̀ ìkínní jẹ́ jásípérì; ìkejì, sáfírù; ìkẹta, kalíkedónì ìkẹrin, emeralídì.

20. Ikarun, sadonikísì; ìkẹfà, kanelíánì; ìkeje, kírisolítì; ìkẹjọ bérílì; ìkẹsan, tọ́pásì; ìkẹwàá, kírísopírasù; ìkọkànlá, jakinítì; ìkejìlá, ámétísítì.

21. Ẹnu-bodè méjèèjìlá jẹ́ pẹ́rílì méjìlá: olúkúlùkù ẹnu-bodè jẹ́ pérílì kan; ọ̀nà ìgboro ìlú náà sì jẹ́ kìkì wúrà, ó dàbí dígí dídán.

22. Èmi kò sì ri tẹḿpílì nínú rẹ̀: nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè ni téḿpílì rẹ̀, àti Ọ̀dọ́-Àgùntàn.

Ka pipe ipin Ìfihàn 21