Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 16:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti inú tẹ́ḿpìlì wá, ń wí fún àwọn ańgẹ́lì, méje nì pé, “Ẹ lọ, ẹ sì tú ìgò ìbínú Ọlọ́run wọ̀nnì sí orí ayé.”

2. Èkínní sì lọ, ó sì tú ìgò tirẹ̀ sí orílẹ̀ ayé: egbò kíkẹ̀ tí ó sì díbàjẹ́ sì dá àwọn ènìyàn tí ó ní àmì ẹranko náà, àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ fún àwòrán rẹ̀.

3. Èkejì sì tú ìgò sínú òkun; ó sì dàbí ẹ̀jẹ̀ òkú ènìyàn: gbogbo ọkàn alàyè sì kú nínú òkun.

4. Ẹ̀kẹ́ta sì tú ìgò tirẹ̀ sínú odò, àti sí orísun àwọn omi; wọ́n sì di ẹ̀jẹ̀.

5. Mo sì gbọ́ ańgẹ́lì ti omi wí pé:“Olódodo ni ìwọ Ẹni Mímọ́ ẹni tí ó ń bẹ,tí ó sì ti wà,nítorí tí ìwọ ṣe ìdájọ́ báyìí.

Ka pipe ipin Ìfihàn 16