Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19:3-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ irú bamítíìsímù wo ni a bamitíìsímù yín sí?”Wọ́n sì wí pé, “Sí bamitíìsímù tí Jòhánù.”

4. Pọ́ọ̀lù sí wí pé, “Nítọ̀ọ́tọ́, ní Jòhánù fi bamitíìsímù tí ìrònúpìwàdà bamitíìsímù, ó ń wí fún àwọn ènìyàn pé, kí wọ́n gba ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn òun gbọ́, èyí sì ni Kírísítì Jésù.”

5. Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, a bamitíìsímù wọn lórúkọ Jéṣù Olúwa.

6. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù sì gbé ọwọ́ lé wọn, Ẹ̀mí Mímọ́ sì bà lé wọn: wọ́n sì ń fọ́ èdè mìíràn, wọ́n sì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀.

7. Iye àwọn ọkùnrin náà gbogbo tó méjìlá.

8. Nígbà tí ó sì wọ inú Sínágọ́gù lọ ó fi ìgboyà sọ̀rọ̀ ni oṣù mẹ́ta, ó ń fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀, ó sì ń yí wọn lọ́kàn padà sí nǹkan tí i ṣe tí ìjọba Ọlọ́run.

9. Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn àwọn mìíràn nínú wọn di líle, tí wọn kò sì gbàgbọ́, tí wọn ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọ̀nà náà níwájú ìjọ ènìyàn, ó lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì ya àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sọ́tọ̀, ó sì ń sọ àsọyé lójoójúmọ́ ni ilé-ìwé Tíráńnù.

10. Èyí n lọ bẹ́ẹ̀ fún ìwọ̀n ọdún méjì; tóbẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn tí ń gbé Éṣíà gbọ́ ọ̀rọ̀ Jésù Olúwa, àti àwọn Júù àti àwọn Gíríkì.

11. Ọlọ́run sì tí ọwọ́ Pọ́ọ̀lù ṣe àwọn àkànṣe iṣẹ́ ìyànu,

12. Tóbẹ́ẹ̀ tí a fi ń mú aṣọ àti ìbàǹtẹ́ ara rẹ̀ tọ àwọn ọlọ́kùnrùn lọ, àrùn sì fi wọ́n sílẹ̀, àwọn ẹ̀mí búburú sì jáde kúrò lára wọn.

13. Ṣùgbọ́n àwọn Júù kan alárìnkiri, alẹ́mìí-èṣù jáde, bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ ni àdábọwọ́ ara wọn, láti pé orúkọ Jésù Olúwa sí àwọn tí ó ni ẹ̀mí búburú, wí pé, “Àwa fi orúkọ Jésù tí Pọ́ọ̀lù ń wàásù fi yín bú.”

14. Àwọn méje kan sì wà, tí wọn ń ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn ọmọ ẹnìkan tí a ń pè ni Síkẹ́fà, Júù, tí í ṣe olórí àlùfáà gíga.

15. Ẹmí búburú náà sì dáhùn, ó ní “Jéù èmi mọ̀ ọ́n, mo sì mọ Pọ́ọ̀lù pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ta ni ẹ̀yin?”

16. Nígbà tí ọkùnrin tí ẹ̀mí búburú náà wà lára rẹ̀ sì fò mọ́ wọn, ó pá kúúrù mọ́ wọn, ó sì borí wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sá jáde kúrò ní ilé náà ní ìhòòhò pẹ̀lú ni ìfarapa.

17. Ìròyìn yìí sì di mímọ̀ fún gbogbo àwọn Júù àti àwọn ará Gíríkì pẹ̀lú tí ó ṣe àtìpó ní Éfésù; ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn, a sì gbé orúkọ Jésù Olúwa ga.

18. Ọ̀pọ̀ àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ sì wá, wọ́n jẹ́wọ́, wọ́n sì fi iṣẹ́ wọn hàn.

19. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn tí ń se alálùpàyídà ni ó kó ìwé wọn jọ, wọ́n dáná sun wọ́n lójú gbogbo ènìyàn: wọ́n sì sirò iye wọn, wọ́n sì rí i, ó jẹ́ ẹgbàámẹ́ẹ̀dọ́gbọ́n ìwọ̀n fàdákà.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 19