Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15:29-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Kí ẹ̀yin fà sẹ̀yìn kúrò nínú ẹran àpabọ òrìṣà, àti nínú ẹ̀jẹ̀ àti nínú ohun ìlọ́lọ́rùn-pa, àti nínú àgbérè: nínú ohun tí, bí ẹ̀yin bá pa ara yín mọ́ kúrò, ẹ̀yin ó ṣe rere.Àlàáfíà.

30. Ǹjẹ́ nígbà tí wọ́n sì fi wọ́n sílẹ̀ láti lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá si Áńtíókù: nígbà tí wọn sì pé àwọn ìjọ pọ̀, wọn fi ìwé náà fún wọn.

31. Nígbà tí wọn sì kà á, wọ́n yọ̀ fún ìtùnú náà.

32. Bí Júdà àti Sílà tìkara wọn ti jẹ́ wòlíì pẹ̀lú, wọ́n fi ọ̀rọ̀ púpọ̀ gba àwọn arákùnrin níyànjú, wọ́n sì mú wọn lọ́kàn le.

33. Nígbà tí wọn sì pẹ́, díẹ̀, àwọn arákùnrin rán wọn padà lọ ni àlàáfíà sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ó rán wọn wá.

34. (Ṣùgbọ́n o wú Sílà láti gbé ibẹ̀.)

35. Pọ́ọ̀lù àti Bánábà sì dúró díẹ̀ ni Ańtíókù, wọ́n ń kọ́ní, wọ́n sì ń wàásù ọ̀rọ̀, Olúwa, àti àwọn púpọ̀ mìíràn pẹ̀lú wọn.

36. Lẹ́yìn ọjọ́ mélóòkán. Pọ́ọ̀lù sì sọ fún Bánábà pé, “Jẹ́ kí a tún padà lọ bẹ àwọn arákùnrin wa wò, bí wọn ti ń ṣe sí ni ìlú gbogbo tí àwa ti wàásù ọ̀rọ̀ Olúwa.”

37. Bánábà sì pinnu rẹ̀ láti mú Jòhánù lọ pẹ̀lú wọn, ẹni tí àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Máàkù.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 15