Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 14:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó sí ṣe, ni Ìkóníónì, Pọ́ọ̀lù àti Bánábà júmọ́ wọ inú sínágọ́gù àwọn Júù lọ, wọ́n sì sọ̀rọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Júù àti àwọn aláìkọlà gbàgbọ́,

2. Ṣùgbọ́n àwọn aláìgbàgbọ́ Júù rú ọkàn àwọn aláìkọlà sókè, wọ́n sì mú wọn ni ọkàn ìkorò sí àwọn arákùnrin náà.

3. Nítorí náà Pọ́ọ̀lù àti Bánábà gbé ibẹ̀ pẹ́, wọ́n ń fi ìgboyà sọ̀rọ̀ nínú Olúwa, ẹni tí ó jẹ̀rìí sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, ó sì yọ̀ǹda kí iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu máa ti ọwọ́ wọn ṣe.

4. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ìlú náà pín sí méjì: apákan dàpọ̀ mọ́ àwọn Júù, apákan pẹ̀lú àwọn àpósítélì.

5. Bí àwọn aláìkọlà, àti àwọn Júù pẹ̀lú àwọn olórí wọn ti fẹ́ kọlù wọ́n láti fi àbùkù kàn wọ́n, àti láti sọ wọ́n ní òkúta,

6. wọ́n gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì sálọ sí Lísírà, àti Dábè, àwọn ìlú Líkáóníà àti sí agbégbé àyíká.

7. Níbẹ̀ ni wọ́n sì ń wàásù ìyìn rere.

8. Ọkùnrin kan sí jókòó ni Lísírà, ẹni tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò mókun, arọ láti inú ìyá rẹ̀ wá, tí kò rìn rí.

9. Ọkùnrin yìí gbọ́ bí Pọ́ọ̀lù ti ń sọ̀rọ̀: ẹni, nígbà tí ó tẹjúmọ́ ọn ti ó sì rí i pé, ó ni ìgbàgbọ́ fún ìmúláradá.

10. Ó wí fún un ní ohùn rara pé, “Dìde dúró ṣánsán lórí ẹsẹ̀ rẹ!” Ó sì ń fò sókè, ó sì ń rìn.

11. Nígbà tí àwọn ènìyàn sì rí ohun tí Pọ́ọ̀lù ṣe, wọ́n gbé ohùn wọn sókè ni èdè Líkáóníà, wí pé, “Àwọn ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wá wá ni àwọ̀ ènìyàn!”

12. Wọn sì pe Bánábà ni Ṣeusi àti Pọ́ọ̀lù ni Hamisi nítorí òun ni olórí ọ̀rọ̀ síṣọ.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 14