Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 1:15-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni Pétérù sí díde dúró láàrin àwọn ọmọ-ẹ̀yìn (iye àwọn ènìyàn gbogbo nínú ìjọ jẹ́ ọgọ́fà)

16. ó w í pé, “Ẹ̀yin ará, ìwé-Mímọ́ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ, èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu Dáfídì nípa Júdásì, tí ó ṣe atọ́nà fún àwọn tí ó mú Jésù:

17. nítorí ọ̀kan nínú wa ni òun ń se tẹ́lẹ̀, òun sì ní ìpín nínú iṣẹ́-ìránṣẹ́ yìí.”

18. (Júdásì fi èrè àìsòótọ́ rẹ̀ ra ilẹ̀ kan; nígbà tí ó sì subú ni ògèdèǹgbé, ó bẹ́ ní agbede-méjì, gbogbo ifun rẹ̀ sì tú jáde.

19. Ó si di mímọ̀ fún gbogbo àwọn ti ń gbé Jerúsálémù; nítorí náà ni wọ́n fi ń pè ilẹ̀ náà ni Ákélídámà ní èdè wọn, èyí sì ni, Ilẹ̀ Ẹ̀jẹ́.)

20. Pétérù sì wí pé, “Nítorí a ti kọ ọ́ nípa rẹ̀ pé nínú Ìwé Ṣáàmù pé,“ ‘Jẹ́ ki ibùjókòó rẹ̀ di ahoro,kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀,’àti,“ ‘ipò rẹ̀ ni kí ẹlòmíràn kí ó gbà.’

21. Nítorí náà, ó di dandan láti yan ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin wọn tí wọn ti ń bá wa rìn ni gbogbo àkókò tí Jésù Olúwa ń wọlé, tí ó sì jáde láàrin wa.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 1