Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Gálátíà 3:6-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Gẹ́gẹ́ bí Ábúráhámù “Ó gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí fún un ní òdodo.”

7. Ẹ jẹ́ kí ó yé é yín nígbà náà pé, àwọn ti ó gbàgbọ́, àwọn náà ní í ṣe ọmọ Ábúráhámù.

8. Bí ìwé-mímọ́ sì tí wí tẹ́lẹ̀ pé, Ọlọ́run yóò dá aláìkọlà láre nípa ìgbàgbọ́, ó tí wàásù ìyìn rere ṣáájú fún Ábúráhámù, ó ń wí pé, “Nínú rẹ̀ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”

9. Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí i ṣe tí ìgbàgbọ́ jẹ́ ẹni alábùkúnfún pẹ̀lú Ábúráhámù olódodo.

10. Nítorí pé iye àwọn tí ń bẹ ni ipa iṣẹ́ òfin ń bẹ lábẹ́ ègún: nítorí tí a tí kọ ọ́ pé, “Ìfibú ni olúkúlùkù ẹni tí kò dúró nínú ohun gbogbo tí a kọ sínú ìwé òfin láti máa ṣe wọ́n.

11. Nítorí ó dánilójú pé, a kò dá ẹnìkẹ́ni láre níwájú Ọlọ́run nípa iṣẹ́ òfin: nítorí pé, olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́.”

12. Òfin kì í sì í ṣe ti ìgbàgbọ́: ṣùgbọ́n “Ẹnikẹ́ni tí ń se wọn yóò yè nípaṣẹ̀ wọn.”

13. Kírísítì ti rà wá padà kúrò lọ́wọ́ ègún òfin, ẹni tí a fi ṣe ègún fún wa: nítorí tí a ti kọ ọ́ pé, “Ìfibú ni olúkúlùkù ẹni tí a fi kọ́ sórí igi.”

Ka pipe ipin Gálátíà 3