Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 12:11-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Gbogbo ìbáwí kò dábì ohun ayọ̀ nísinsìn yìí bí kò ṣe ìbànújẹ́; ṣùgbọ́n níkẹ́yìn yóò so èso àlàáfíà fún àwọn tí a tọ́ nípa rẹ̀, àní èso òdodo.

12. Nítorí náà ẹ na ọwọ́ tí o rọ, àti èékún àìlera;

13. “Kí ẹ sì ṣe ipa-ọ̀nà tí ó tọ́ fún ẹsẹ̀ yin,” kí èyí tí ó rọ má bá a kúrò lórí ike ṣùgbọ́n kí a kuku wò ó sàn.

14. Ẹ máa lépa àlàáfíà pẹ̀lú ènìyàn gbogbo, àti ìwà mímọ́, láìsí èyí yìí kò sí ẹni tí yóò rí Olúwa:

15. Ẹ máa kíyèsára kí ẹnikẹ́ni má ṣe kùnà oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run; kí “Gbòngbò ìkoro” kan máa ba hù sókè kí ó sì yọ yín lẹ́nu, ọ̀pọ̀lọpọ̀ a sì ti ipa rẹ̀ di àìmọ́.

16. Kí o má bá à si àgbérè kan tàbí aláìwà-bí-Ọlọ́run bi Èsau, ẹni tí o titorí òkèlè oúnjẹ kan ta ogún ìbí rẹ̀.

17. Nítorí ẹ̀yin mọ pé lẹ̀yìn náà, nígbà tí ó fẹ láti jogún ìbùkún náà, a kọ̀ ọ́, nítorí kò ri àyè ìronupìwàdà, bí o tilẹ̀ kẹ pé ó fi omijé wa a gidigidi.

18. Nítorí ẹ̀yin kò wá òkè tí a lè fi ọwọ́ kàn, àti ti iná ti ń jó, àti ti ìṣúdudu àti òkùnkùn, àti ìjì.

19. Àti ìró ìpè, àti ohùn ọ̀rọ̀, èyí tí àwọn tí o gbọ́ bẹ̀bẹ̀ pé, kí a má ṣe sọ ọ̀rọ̀ si i fún wọn mọ́:

20. Nítorí pé ara wọn kò lè gba ohun tí ó palaṣẹ, “Bí o tilẹ̀ jẹ ẹranko ni o farakan òkè náà, a o sọ ọ ni òkúta, tàbí a o gun un ní ọ̀kọ̀ pa.”

21. Ìran náà sì lẹ̀rù to bẹ́ẹ̀ tí Móṣè wí pé, “Ẹrù ba mi gidigidi mo sì wárìrì.”

22. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wá sí òkè Síónì, àti sí ìlú Ọlọ́run alààyè, ti Jerúsálémù ti ọ̀run, àti si ẹgbẹ́ àwọn áńgẹ́lì àìníye,

23. Si àjọ ńlá tí ìjọ àkọ́bí tí a ti kọ orúkọ wọn ni ọ̀run, àti sọ́dọ̀ Ọlọ́run onídájọ́ gbogbo ènìyàn, àti sọ́dọ̀ àwọn ẹ̀mí olóòtọ́ ènìyàn tí a ṣe ni àṣepé, o

24. Àti sọ́dọ̀ Jésù alárinà májẹ̀mú titun, àti si ibi ẹ̀jẹ̀ ìbùwọ́n ni, ti ń sọ̀rọ̀ ohun tí ó dára ju ti Ábélì lọ.

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 12