Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 10:27-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Bí kò ṣe ìrètí ìdájọ́ tí ó ba ní lẹ̀rù, àti ti ìbínú ti o múná, tí yóò pa àwọn ọ̀ta run.

28. Ẹnikẹ́ni tí ó ba gan òfin Móṣè, ó kú láìsí àánú nípa ẹ̀rí ẹni méjì tàbí mẹ́ta:

29. Mélòómélòó ni ẹ rò pé a o jẹ Olúwa rẹ̀ ní ìyà kíkan, ẹni tí o tẹ ọmọ Ọlọ́run mọ́lẹ̀ tí ó sì ti ka ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú ti a fi sọ ọ́ di mímọ́ si ohun àìmọ́, tí ó sì ti kẹgan ẹmi oore òfẹ́.

30. Nítorí àwa mọ ẹni tí o wí pé: Ẹ̀san niti èmi, Olúwa wí pé, “Èmi o gbẹ̀san.” Àti pẹ̀lú, “Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.”

31. Ohun ẹ̀rù ni láti ṣubú sí ọwọ́ Ọlọ́run alààyè.

32. Ṣùgbọ́n ẹ rántí ọjọ́ ìṣáájú nínú èyí tí, nígbà tí a ti ṣi yin lójú, ẹ fi ara da wàhálà ńlá ti ìjìyà;

33. Lápakan, nígbà tí a ṣọ yín di ìran wíwò nípa ẹ̀gàn àti ìpọ́njú; àti lápakan, nígbà tí ẹ̀yin di ẹ̀gbẹ àwọn tí a ṣe bẹ́ẹ si.

34. Nítorí ẹ̀yin bá àwọn tí ó wà nínú ìdè kẹ́dùn, ẹ sì fi ayọ̀ gba ìkólọ ẹrù yin, nítorí ẹ̀yin mọ nínú ara yin pé, ẹ ni ọrọ̀ tí ó wà títí, tí ó sì dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.

35. Nítorí náà ẹ má ṣe gbé ìgboyà yín sọnù, èyí ti o ni èrè ńlá.

36. Nítorí ẹ̀yin kò le ṣe aláìní suuru, nítorí ìgbà tí ẹ̀yin bá ti ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run tan kí ẹ̀yin le gba ìlérí náà.

37. Nítorí ni ìwọ̀n ìgbà díẹ̀ sí i,“Ẹni náà ti ń bọ̀ yóò dé, kí yóò sì jáfara.

38. Ṣùgbọ́n olódodo ni yóò yè nípa ìgbàgbọ́:Ṣùgbọ́n bí o ba fà sẹ́yìn,ọkàn mi kò ní inú dídùn sí i.”

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 10