Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 10:11-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Àti olukulùkù àlùfáà sì ń dúró lójoojúmọ́ láti ṣiṣẹ́ ìsìn, ó sì ń ṣe ẹbọ kan náà nígbàkúgbà, tí kò lè mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò láé:

12. Ṣùgbọ́n òun, lẹ̀yìn ìgbà tí o ti rú ẹbọ kan fún ẹ̀ṣẹ̀ títí láé, o jòkòó lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run;

13. Láti ìgbà náà, ó rétí títí a o fi àwọn ọ̀ta rẹ̀ ṣe àpótí itísẹ̀ rẹ̀.

14. Nítorí nípa ẹbọ kan a ti mú àwọn tí a sọ di mímọ́ pé títí láé.

15. Ẹ̀mí mímọ́ sì ń jẹri fún wa pẹ̀lú: Nítorí lẹ̀yìn tí ó wí pé,

16. “Èyí ni májẹ̀mú ti èmi o ba wọn dálẹ́hìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí,èmi o fi òfin mi sí wọn ní ọkàn,inú wọn pẹ̀lú ni èmi o sì kọ wọn sí.”

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 10