Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Tímótíù 4:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ṣùgbọ́n Olúwa gba ẹjọ́ mi rò, ó sì fún mi lágbára; pé nipasẹ̀ mi kí a lè wàásù náà ní àwàjálẹ̀, àti pé kí gbogbo àwọn aláìkọlà lè gbọ́; a sì gbà mí kúrò lẹ́nu kìnìún náà.

18. Olúwa yóò yọ mí kúrò nínú iṣẹ́ bubúrú gbogbo, yóò sì gbà mí dé inú ìjọba rẹ̀; ẹni ti ògo wà fún láé àti láéláé. (Àmín).

19. Kí Parísíkà àti Àkúílà, àti ilé Onésífórù.

20. Érásítù wà ní Kọ́ríntí: ṣùgbọ́n mo fi Tírófímù sílẹ̀ ni Mílétù nínú àìsàn.

21. Sa ipá rẹ láti tètè wá ṣáájú ìgbà òtútù. Éúbúlù kí ọ, àti Páúdánì, àti Línù, Kíláúdíà, àti gbogbo àwọn ará-kùnrin.

22. Kí Olúwa wà pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú yín. (Àmín).

Ka pipe ipin 2 Tímótíù 4