1. Nítorí náà mo pàṣẹ fún ọ níwájú Ọlọ́run, àti Kírísítì Jésù, ẹni tí yóò ṣe ìdájọ́ alààyè àti òkú, àti nítorí ìfarahàn rẹ̀ àti ìjọba rẹ̀.
2. Wàásù ọ̀rọ̀ náà, ṣe àìsinmi ní àkókò tí ó wọ̀, àti àkókò ti kò wọ̀; bániwí, ṣe ìtọ́ni, gbani níyànjú pẹ̀lú ìpamọ́ra àti ẹ̀kọ́ gbogbo.
3. Nítorí pé ìgbà yóò dé, tí wọn kì yóò lè gba ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro, ṣùgbọ́n bí wọ́n ti jẹ́ ẹni tí etí ń rin, wọn ó lọ kó oluko jọ fún ara wọn nínú ìfẹ́kùfẹ́ ara wọn.
4. Wọ́n ó sì yí etí wọn padà kúrò nínú òtítọ́, wọn ó sì yípadà sí ìtàn asán.
5. Ṣùgbọ́n máa faradà ìpọ́nju, ṣe iṣẹ́ ẹ̀fáńjẹ́lísítì, ṣe iṣẹ́ rẹ láṣepé.
6. Nitorí à ń fí mi rúbọ nisínsinyìí, àtilọ mi sì súnmọ́ etíle.
7. Èmi ti ja ìjà rere, èmi tí parí iré-ìje mi, èmi ti pa ìgbàgbọ́ mọ́;
8. Láti ìsinsinyìí lọ a fi adé òdodo lélẹ̀ fún mi, tí Olúwa onídàjọ́ òdodo, yóò fífún mi ni ọjọ́ náà kì í sì í ṣe kìkì èmi nìkan ṣùgbọ́n pẹ̀lú fún gbogbo àwọn tí ó ti fẹ́ ìfarahàn rẹ̀.
9. Sa ipá rẹ láti tètè tọ̀ mí wá.
10. Nítorí Démà ti kọ̀ mí sílẹ̀, nitorí ó ń fẹ́ ayé yìí, ó sì lọ sí Tẹsalóníkà; Kírésíkénì sí Gálátíà, Títù sí Dalimátíà.
11. Lúùkù nìkan ni ó wà pẹ̀lú mi, mú Máàkù wá pẹ̀lú rẹ: nítorí ó wúlò fún mi fún iṣẹ́-ìránṣẹ́.