Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Tímótíù 3:9-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ṣùgbọ́n wọn kì yóò lọ ṣíwájú ju bẹ́ẹ̀ lọ: Nítorí òmùgọ̀ wọn yóò farahàn fún gbogbo ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ti àwọn méjì yìí náà, ti yọrí si.

10. Ṣùgbọ́n ìwọ ti mọ ẹ̀kọ́ mi, ìgbésí ayé mi, ìpinnu, ìgbàgbọ́, ìpamọ́ra, ìfẹ́-ni sùúrù.

11. Inúnibíni, ìyà; àwọn ohun tí ó dé bá mi ní Ańtíókù, Ní Ìkóníónì àti ní Lísítírà; àwọn inúnibíni tí mo faradà: Olúwa sì gbà mi kúrò nínú gbogbo wọn.

12. Nítòótọ́, gbogbo àwọn tí ó fẹ́ máa gbé ìgbé-ayé ìwà-bí-Ọlọ́run nínú Kírísítì Jésù yóò faradà inúnibíni

13. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú, àti àwọn ẹlẹ̀tàn yóò máa burú síwajú sí i, wọn ó máa tan-nijẹ, a ó sì máa tàn wọ́n jẹ.

14. Ṣùgbọ́n ìwọ dúró nínú nǹkan wọ̀nyí tí ìwọ ti kọ́, tí a sì ti jẹ́ kí ojú rẹ dá ṣáṣá sí, kí ìwọ sì mọ̀ ọ̀dọ̀ ẹni tí ìwọ gbé kọ́ wọn.

15. Àti pé láti ìgbà ọmọdé ni ìwọ ti mọ ìwé-Mímọ́, tí ó lè sọ ọ́ di ọlọ́gbọ́n sí ìgbàlà nípasẹ́ ìgbàgbọ́ nínú Kírísítì Jésù.

16. Gbogbo ìwé-Mímọ́ ni ó ní ìmísí Ọlọ́run tí ó sì ní èrè fún ẹ̀kọ́, fún ìbániwí, fún ìtọ́ni, fún ìkọ́ni tí ó wà nínú òdodo.

Ka pipe ipin 2 Tímótíù 3