Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Tímótíù 3:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ṣùgbọ́n èyí ni kí o mọ̀: pé ní ìkẹyìn ọjọ́ ìgbà ewu yóò dé.

2. Nitori àwọn ènìyàn yóò jẹ́ olùfẹ́ ti ara wọn, olùfẹ́ owó, afọ́nnu, agbéraga, asọ̀rọ̀-búburú, aṣàìgbọ́ràn sí òbí, aláìlọ́pẹ́, aláìmọ́.

3. Aláìnífẹ̀ẹ́, aláìlè-dáríjí-ni, abanijẹ́, aláìlè-kó-rawọn-níjánu, òǹrorò, aláìnífẹ̀ẹ́ ohun rere,

4. oníkúpani, alágídí, ọlọ́kàn gíga, olùfẹ́ fàájì ju olùfẹ́ Ọlọ́run lọ.

5. Àwọn tí wọn ní àfarawé ìwá-bí-Ọlọ́run, ṣùgbọ́n tí wọn sẹ́ agbára rẹ̀; yẹra kúrò lọ́dọ̀ àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú.

6. Nítorí nínú irú èyí ni àwọn ti ń rákò wọ inú ilé, tí wọ́n sì ń di àwọn obìnrin aláìlọ́gbọ́n tí a di ẹ̀ṣẹ̀ rù ní ìgbèkùn, tí a sì ń fi onírúurú ìfẹ́kùfẹ̀ẹ́ fà kiri

7. Wọ́n ń fi ìgbà gbogbo kẹ́kọ̀ọ́, wọ́n kò sì lè dé ojú ìmọ̀ òtítọ́.

8. Ǹjẹ́ gẹ́gẹ́ bí Jánésì àti Jámbérì ti kọ ojú ìjà sí òtítọ́: àwọn ènìyàn tí inú wọn díbàjẹ́, àwọn ẹni ìtanù ní ti ọ̀ràn ìgbàgbọ́.

9. Ṣùgbọ́n wọn kì yóò lọ ṣíwájú ju bẹ́ẹ̀ lọ: Nítorí òmùgọ̀ wọn yóò farahàn fún gbogbo ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ti àwọn méjì yìí náà, ti yọrí si.

10. Ṣùgbọ́n ìwọ ti mọ ẹ̀kọ́ mi, ìgbésí ayé mi, ìpinnu, ìgbàgbọ́, ìpamọ́ra, ìfẹ́-ni sùúrù.

11. Inúnibíni, ìyà; àwọn ohun tí ó dé bá mi ní Ańtíókù, Ní Ìkóníónì àti ní Lísítírà; àwọn inúnibíni tí mo faradà: Olúwa sì gbà mi kúrò nínú gbogbo wọn.

Ka pipe ipin 2 Tímótíù 3