Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Tẹsalóníkà 2:5-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ṣé ẹ̀yin kò rántí pé nígbà tí mo wà pẹ̀lú yín, mo ń sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún-un yín.

6. Àti pé nísinyìí, ẹ̀yín mọ ohun tí ń dá a dúró, kí a bá a lè fi í hàn ní àkókò rẹ̀ gan an.

7. Nítorí agbára ìkọ̀kọ̀ ẹni ẹ̀ṣẹ̀ ti ń ṣiṣẹ́; ṣùgbọ́n ẹni tí ń dènà yóò máa ṣe bẹ́ẹ̀ títí a ó fi mú-un kúrò ní ọ̀nà.

8. Nígbà náà ni a ó fi ẹni ẹ̀ṣẹ̀ hàn, ẹni tí Jésù Olúwa yóò fi èémí ẹnu rẹ̀ pa, tí yóò sì fi ọlá ìpadàbọ̀ rẹ̀ parun.

9. Wíwá ẹni ẹ̀ṣẹ̀ yóò rí bí iṣẹ́ Sàtánì, gbogbo èyí tí a fihàn gẹ́gẹ́ bí àdàmọ̀dì iṣẹ́-ìyanu, àdàmọ̀dì àmì àti àdàmọ̀dì idán,

10. Ní gbogbo ọ̀nà búburú tí a fi ń tan àwọn tí ń ṣègbé jẹ. Wọ́n ṣègbé nítorí wọ́n kọ̀ láti fẹ́ràn òtítọ́ kí wọn sì di ẹni ìgbàlà.

11. Nítorí ìdí èyí, Ọlọ́run rán ohun tó ń ṣiṣẹ́ ìsìnà sí wọn kí wọn lè gba èké gbọ́,

12. Kí wọn kí ó lè gba ìdálẹ́bi, àní àwọn tí kò gba òtítọ́ gbọ́, ṣùgbọ́n tí wọ́n ní inú-dídùn nínú ìwà-búburú.

13. Ṣùgbọ́n, ohun tí ó tọ́ fún wa ni láti máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nígbà gbogbo nítorí yín, ará olùfẹ́ ní ti Olúwa, nítorí láti ìbẹ̀rẹ̀ ni Ọlọ́run ti yàn yín sí ìgbàlà nípa ìṣọdi-mímọ́ ti Ẹ̀mí àti nípa gbígba òtítọ́ gbọ́.

14. Òun ti pè yín sí èyí nípa ìyìn rere wa, kí ẹ̀yin kí ó lè pín nínú ògo Jésù Kírísítì Olúwa wa.

15. Nítorí náà ará, ẹ dúró sinsin, kí ẹ sì di àwọn ẹ̀kọ́ wọ̀n-ọn-nì tí a kọ́ yín mú, yálà nípa ọ̀rọ̀ ẹnu tàbí lẹ́tà.

Ka pipe ipin 2 Tẹsalóníkà 2