Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 11:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mo rò wí pé ẹ ó farada díẹ̀ nínú ìwà òmùgọ̀ mi ṣùgbọ́n ẹ tilẹ̀ ti rí ṣe bẹ́ẹ̀.

2. Nítorí pé èmi ń jówu lórí i yín ní ti owú ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run: nítorí tí mo ti fì yín fún ọkọ kan, kí èmi bà á lè mú yín wá bí wúndíá tí ó mọ́ sọ́dọ̀ Kírísítì.

3. Ṣùgbọ́n ẹ̀rù ń bà mí, kí ó má bà á jẹ́ pé, bí ejò ti tan Éfà jẹ́ nípaṣẹ̀ àrékérekè rẹ̀, a lè mú ọkàn yín sáko lọ kúrò nínú òtítọ́ yín àti ìfarajìn fún Kírísítì.

4. Nítorí bí ẹnìkan bá wá tí ó sì wàásù Jésù mìíràn, yàtọ̀ sí èyí tí a ti wàásù rí tàbí bí ẹ̀yin bá gba ẹ̀mí mìíràn, yàtọ̀ sí èyí tí ẹ ti gbà tàbí ìyìn rere mìíràn yàtọ̀ sí èyí tí ẹ ti gbà, tí ẹ sì ti yára tẹ́wọ́ gbà á.

5. Nítorí mo rò pé èmi kò rẹ̀yìn ní ohunkohun sí àwọn àgbà Àpósítélì.

6. Bí mo tilẹ̀ jẹ́ òpè nínú ọ̀rọ̀ sísọ, kì í ṣe nínú ìmọ̀; Ní ọ̀nàkọnà ni àwa ti fi èyí hàn dájúdájú fún yín nínú ohun gbogbo.

7. Tàbí ẹ̀ṣẹ̀ ni mo dá bí èmi ti ń rẹ ara mí sílẹ̀ kí a lè gbé yín ga, nítorí tí mo wàásù ìyìn rere Ọlọ́run fún un yín lọ́fẹ̀ẹ́.

8. Èmí ń ja ìjọ mìíràn ni olè nípa gbigba ìpèsè owó ki èmi bà á lè sìn yín.

9. Nígbà tí mo sì wà pẹ̀lú yín, tí mo sì ṣe aláìní, èmi kò dẹ́rù pa ẹnikẹ́ni: nítorí ohun tí mo ṣe aláìní ni àwọn ará tí ó ti Makedóníà wá ti mú wá. Bẹ́ẹ̀ ni nínú ohun gbogbo mo pa ara mi mọ́ láti má ṣe jẹ́ ẹrù fún yín, èmi yóò sì pa ara mi mọ́ bẹ́ẹ̀.

10. Ó jẹ́ òtítọ́, Kírísítì tí ń bẹ nínú mi pé kò sí ẹni tí ó lè dá mi lẹ́kun ìṣògo yìí ni gbogbo ẹkùn Ákáyà.

11. Nítorí kín ni? Nítorí èmi kò fẹ́ràn yín ni bí? Ọlọ́run mọ̀.

12. Ṣùgbọ́n ohun ti mo ń ṣe ni èmi yóò sì máa ṣe, kí èmi lè mú ẹ̀fẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn tí wọn ń fẹ́ ṣẹ̀fẹ̀, pé nínú ohun tí wọ́n ṣògo, kí a lè rí wọn gẹ́gẹ́ bí àwa.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 11