Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 10:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ṣùgbọ́n èmi Pọ́ọ̀lù fúnra mi fi inú tútù àti ìwà pẹ̀lẹ́ Kírísítì bẹ̀ yín, èmi ẹni ìrẹ̀lẹ̀ lójú yín nígbà tí mo wà láàárin yín, ṣùgbọ́n nígbà tí èmi kò sí, mo di ẹni ìgboyà sí yín.

2. Ṣùgbọ́n èmi bẹ̀ yín pé nígbà tí mo wà láàárin yín, kí èmi baà lè lo ìgboyà pẹ̀lú ìgbẹ́kẹ̀lé náà, eléyìí tí mo ti fọkàn sí láti fi dojúkọ àwọn kan, ti ń fúra sí wa bí ẹni tí ń rìn nípa ti ara.

3. Nítorí pé, bí àwa tilẹ̀ rìn nípa ti ara, ṣùgbọ́n àwa kò jagun nípa ti ara.

4. Nítorí ohun ìjà wa kì í ṣe ti ara, ṣùgbọ́n ó lágbára nínú Ọlọ́run láti wó ibi gíga palẹ̀.

5. Àwa ń sọ gbogbo èrò àti gbogbo ohun gíga ti ń gbe ara rẹ̀ ga sí ìmọ̀ Ọlọ́run, àwa sì ń di gbogbo èrò ní ìgbékùn wá sí ìtẹríba fún Kírísítì.

6. Àwa sì ti murá tan láti jẹ gbogbo àìgbọ́ràn níyà, nígbà tí ìgbọ́ràn yín bá pé.

7. Ẹ̀yin sì ń wo nǹkan gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fi hàn lóde. Bí ẹnikẹ́ni bá ní ìgboyà nínú ara rẹ̀, ti Kírísítì ni òun, kí ó tún rò lẹ́ẹ̀kan si pé, bí òun ti jẹ́ ti Kírísítì, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwa pẹ̀lú jẹ́ ti Kírísítì.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 10