Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 1:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Pọ́ọ̀lù Àpósítélì Jésù Kírisítì nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, àti Tímótíù arákùnrin wá, sí ìjọ Ọlọ́run tí ó wà ní Kọ́ríńtí pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn-mímọ́ tí ó wà ní gbogbo Ákáyà:

2. Oore-ọ̀fẹ́ si yín àti àlàáfíà làti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Jésù Kírísítì Olúwa.

3. Olùbùkún ni Ọlọ́run, àti Baba Jésù Kírísítì Olúwa wa, Baba ìyọ́nú, àti Ọlọ́run ìtùnú gbogbo;

4. Ẹni tí ń tù wá nínú ni gbogbo ìdààmú wa, ki àwa lè máa pẹ̀lú tu àwọn tí ó wá nínú ìdààmú nínú, nípá ìtùnú náà ti a fi ń tú àwa fúnra wa nínú làti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.

5. Nítorí pé bí ìjìyà Kírísítì ti sínú ayé wa,, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ nì ìtùnú wa dí púpọ pẹ̀lú nípa Kírísítì.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 1