Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 9:2-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ní ìrònú àwọn ẹlòmíràn, èmi kì í ṣe àpósítélì. Dájúdájú àpósítélì ni mo jẹ́ fún un yín, tí n kì bá ṣe fún àwọn ẹlòmíràn. Nítorí èdìdì iṣẹ́ àpósítélì mi ni ẹ̀yin jẹ́ nínú Olúwa.

3. Èyí ni ìdáhùn mi sí àwọn tí ń béèrè ẹ̀tọ́ Àpósítélì mi.

4. Ṣé a kò ní ẹ̀tọ́ láti máa jẹ àti láti máa mu bí?

5. Ṣé àwa kò ní ẹ̀tọ́ láti máa mú ìyàwó tí í se onígbàgbọ́ káàkiri gẹ́gẹ́ bí àwọn Àpósítélì mìíràn? Àti bí arákùnrin Olúwa, àti Kéfà.

6. Ṣé kìkì Bánábà àti èmi ló yẹ kí a máa ṣisẹ́ bọ́ ara wa ni?

7. Ta ni ó síṣẹ́ ogun nígbà tí ó sanwo ara rẹ̀? Ta ní gbin ọgbà àjàrà tí kì í jẹ nínú èso rẹ̀?, Tàbí ta ní ń bọ ọ̀wọ́-ẹran tí kì í sí ì jẹ nínú wàrà ọ̀wọ́-ẹran?

8. Èmi ha sọ nǹkan wọ̀nyí bí ènìyàn? Tàbí òfin kò wí bákan náà bì?

9. Nítorí nínú òfin tí Ọlọ́run fún Mósè, ni a tí kọ ọ́ pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń pakà nínú oko rẹ̀ lẹ́nu mọ́.” Ǹjẹ́ màlúù ni Ọlọ́run n ṣe ìtọ́jú rẹ̀ bi?

10. Dájúdájú ó sọ eléyìí fún wa pé, nítorí wa ni a se kọ̀wé yìí kí ẹni tí ń tulẹ̀ lè máa tulẹ̀ ní ìrètí àti ẹni tí ń pakà lè ni ìretí láti ní ipin nínú ìkórè.

11. A ti fún irúgbìn èso ẹ̀mí sìnú ọkàn yín. Ẹ rò pé ó pọ̀jù fún wa tàbí ẹ kà á sí àṣejù, láti béèré fún oúnjẹ àti aṣọ fún àyọrísí iṣẹ́ wa bí?

12. Bí àwọn ẹlòmírán bá ní ẹ̀tọ́ tí ìrànlọ́wọ́ sì wá láti ọ̀dọ̀ yín, àwa ha kọ́ ni ó tọ́ sí jù?Ṣùgbọ́n àwa kò lo agbára yìí ṣùgbọ́n àwa faradà ohun gbogbo, kí àwa má baà ṣe ìdènà fún ìyìn rere Kírísítì.

13. Ǹjẹ́ ó yé e yín pé Ọlọ́run sọ fún àwọn tí ó ń siṣẹ́ nínú tẹ́ḿpìlì pé kí wọ́n mú oúnjẹ tàbí àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n mú wá fún òun, làti fi se ìtọ́ju ara wọn? Àti àwọn tí ń dúró tí pẹpẹ wọn a máa se àjọpín pẹ̀lú pẹpẹ.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 9