Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 2:12-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Àwa kò gbà ẹ̀mí ti ayé yìí, bí kò ṣe Ẹ̀mí ẹni tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wa, kí a lè ní òye ohun tí Ọlọ́run fi fún wa lọ́fẹ̀ẹ́.

13. Èyí ni àwa ń wí, kì í e èyí tí a ń kọ nípa ọ̀rọ̀ ọgbọ́n ènìyàn, ṣùgbọ́n èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ fi ń kọ ènìyàn, èyí tí a ń fi ohun Ẹ̀mí wé ohun Ẹ̀mí.

14. Ẹnikẹ́ni tí kò bá jẹ́ ti Ẹ̀mí kò lè gba àwọn ohun tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mi Mímọ́, nítorí wọ́n jẹ́ ohun wèrè sí, kò sì le ye e, nítorí nípa tí Ẹ̀mí ní a fi ń wádìí wọn.

15. Ẹni tí ẹ̀mí ń ṣe ìdájọ́ ohun gbogbo, ṣùgbọ́n òun fúnra rẹ̀ ni a kò ti ọwọ́ ènìyàn dá lẹ́jọ́:

16. “Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa,ti yóò fi máa kọ́ Ọ?”Ṣùgbọ́n àwa ní inú Kírísítì.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 2