Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 10:29-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Nǹkan tí ó ṣe pàtàkì ní irú ipò yìí ni ẹ̀rí ọkàn àti èrò ọkùnrin náà, nítorí kì í ṣe ẹ̀rí ọkàn ẹlòmìíràn ní a ó fi dá òmìnira mi lẹ́jọ́.

30. Bí èmi ba fi ọpẹ́ jẹ ẹ́, è é ṣe tí a fì ń sọ̀rọ̀ mi ní búbúrú nítorí ohun tí èmi dúpẹ́ fún.

31. Nítorí náà tí ẹ̀yin bá jẹ tàbí tí ẹ bá mu tàbí ohunkohun tí ẹ̀yin bá sè, e máa ṣe gbogbo rẹ̀ fún ògo Ọlọ́run.

32. Nítorí náà, má ṣe jẹ́ òkúta ìkọ̀sẹ̀ (tí ó lè gbé ẹlòmíràn subú) ìbá à ṣe Júù tàbí Gíríkì tàbí ìjọ Ọlọ́run rẹ̀.

33. Bí ṣè n gbìyanjú láti tẹ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan lọ́rùn nínú gbogbo nǹkan tí mo bá ń ṣe láì wa ohun rere fún ara mi bí kò ṣe ti ènìyàn púpọ̀ kí ó lè ṣe é ṣe fún wọn láti le ní ìgbàlà.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 10