Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 1:16-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. (Bẹ́ẹ̀ ni, mo tún tẹ ìdílé Sítéfánà bọmi; lẹ́yìn èyí, èmí kò rántí pé mo tẹ ẹnikẹ́ni bọmi mọ́ níbikíbi).

17. Nítorí Kírísítì kò rán mi láti máa ṣe ìtẹ̀bọmi, ṣùgbọ́n Ó rán mi láti máa wàásù ìyìn rere: kì í ṣe nípa ọgbọ́n ènìyàn, kí a máa ṣe sọ àgbélébú Kírísítì dí aláìlágbára.

18. Nítorí pé òmùgọ̀ ni ọ̀rọ̀ àgbélébùú jẹ́ sí àwọn tí ń sègbé, ṣùgbọ́n fún àwa tí a ń gbàlà ó jẹ́ agbára Ọlọ́run

19. Nítorí tí kọ ọ́ pé:“Èmi yóò pa ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n run,òye àwọn olóye ni Èmi yóò sọ di asán.”

20. Àwọn ọlọ́gbọ́n ha dá? Àwọn ọ̀mọ̀wé ha dà? Àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ ayé yìí ha dà? Ọlọ́run kò ha ti sọ ọgbọ́n ayé yìí di òmùgọ̀?

21. Nítorí pé, nínú ọgbọ́n Ọlọ́run, ayé kò le mọ̀ òun nípa ọgbọ́n àti ìṣeféfé wọn. Ó sì gba gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́ là nípa ìwàásù tí àwọn aráyé pè ní òmùgọ̀ àti ọ̀rọ̀ ọ yẹ̀yẹ́.

22. Nítorí pé àwọn Júù ń bèrè àmì, àwọn Gíríkì sí ń ṣàfẹ́rí ọgbọ́n:

23. ṣùgbọ́n àwọn ń wàásù Kírísítì ti a kàn mọ́ àgbélébùú, òkúta ìkọ̀sẹ̀ àwọn Júù àti òmùgọ̀ fún àwọn kèfèrí.

24. ṣùgbọ́n sí àwọn tí Ọlọ́run tí pè, àti àwọn Júù àti àwọn Gíríkì, Kírísítì ni agbára Ọlọ́run, àti ọgbọ́n Ọlọ́run.

25. Nítorí pé òmùgọ̀ Ọlọ́run jù ọgbọ́n ènìyàn lọ; àti aláìlera Ọlọ́run ni agbára jù ìlera ènìyàn lọ.

26. Ará, ẹ kíyèsí ohun tí nígbà tí a pè yín. Bí ó ti ṣe pé, kì í ṣe ọ̀pọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn nípa ti ara, kí í ṣe ọ̀pọ̀ àwọn alàgbà, kì ì ṣe ọ̀pọ̀ àwọn ọlọ́lá ni a pè.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 1