Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Jòhánù 2:26-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Nǹkan wọ̀nyí ni mo kọ̀wé sí yín ní ti àwọn tí wọ́n fẹ́ kó o yín sìnà.

27. Ṣùgbọ́n ní ti ẹ̀yin ìfóróró-yàn tí gba lọ́wọ́ rẹ̀ sì ń gbé inú yín, ẹ̀yin kò tún nílò pé kí ẹnìkan kọ yín. Ṣùgbọ́n bí ìfòróró-yàn náà ti ń kọ́ yín ní ohun gbogbo tí o jẹ́ òtítọ́, tí kì í sì í ṣe èké, àní gẹ́gẹ́ bí ó sì ti kọ́ yín, ẹ máa gbé inú rẹ̀.

28. Àti nísinsin yìí, ẹ̀yin ọmọ mi ọ̀wọ́n, ẹ máa gbé inú rẹ̀, pé nígbà tí òun ó bá farahàn, kí a lè ni ìgboyà níwájú rẹ̀, kí ojú má sì tì wá níwájú rẹ̀ ni ìgbà wíwá rẹ̀.

29. Bí ẹ̀yin ba mọ́ pé olódodo ni òun, ẹ mọ pé a bí olúkúlùkù ẹni tí ń ṣe òdodo nípa rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Jòhánù 2