1. Ó sì fí Jóṣúà olorí àlùfáà hàn mí, ó dúró níwájú ańgẹ́lì Olúwa, Sátanì sí dúró lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ láti kọjú ìjà sí i.
2. Olúwa si wí fún Sátanì pé, “Olúwa bá ọ wí ìwọ Sátanì; àní Olúwa tí ó ti yan Jérúsálẹ́mù, yóò bá ọ wí, igi inà kọ́ ni èyí tí a mú kúrò nínú iná?”
3. A sì wọ Jóṣúà ni àṣọ èérí, ó sì dúró níwájú ańgẹ́lì náà.